1 Sámúẹ́lì 26:10-13 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

10. Dáfídì sì wí pé, “Bí Olúwa tí ń bẹ Olúwa yóò pa á, tàbí ọjọ́ rẹ̀ yóò sì pé tí yóò kú, tàbí òun ó sọ̀kalẹ̀ lọ sí ibi ìjà yóò sì ṣègbé níbẹ̀.

11. Olúwa má jẹ́ kí èmi na ọwọ́ mi sí ẹni àmì òróró Olúwa: ǹjẹ́ èmi bẹ̀ ọ́, mú ọ̀kọ̀ náà tí ń bẹ níbi tìmùtìmù rẹ̀, àti ìgò omi kí a sì máa lọ.”

12. Dáfídì sì mú ọ̀kọ̀ náà àti ìgò omi náà kúrò níbi tìmùtìmù Ṣọ́ọ̀lù: wọ́n sì bá tiwọn lọ, kò sì sí ẹnìkan tí ó rí i, tàbí tí ó mọ̀: kò sì sí ẹnikàn tí ó jí; gbogbo wọn sì sùn; nítorí pé oorun ìjìká láti ọdọ Olúwa wá ti ṣubú lù wọ́n.

13. Dáfídì sì rékọjá sí ìhà kejì, ó sì dúró lórí òkè kan tí ó jìnnà réré; àlàfo kan sì wà láàrin méjì wọn:

1 Sámúẹ́lì 26