1 Sámúẹ́lì 24:16-20 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

16. Ó sì ṣe, nígbà tí Dáfídì sì dákẹ́ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí fún Ṣọ́ọ̀lù, Ṣọ́ọ̀lù sì wí pé, “Ohùn rẹ ni èyí bí, Dáfídì ọmọ mi?” Ṣọ́ọ̀lù sì gbé ohùn rẹ̀ sòkè, o sunkún.

17. Ó sì wí fún Dáfídì pé, “Ìwọ ṣe olódodo jù mí lọ; nítorí pé ìwọ ti fi ire san án fún mi, èmi fi ibi san án fún ọ.

18. Ìwọ sì fi oore tí ìwọ ti ṣe fún mi hàn lónìí: nígbà tí ó jẹ́ pé, Olúwa ti fi èmi mi lé ọ lọ́wọ́, Ìwọ kò sì pa mí.

19. Nítorí pé bí ènìyàn bá rí ọta rẹ̀, ó lè jẹ́ kí ó lọ ní àlàáfíà bí? Olúwa yóò sì fi ire san èyí ti ìwọ́ ṣe fún mi lónìí.

20. Wò ó, èmi mọ̀ nísinsin yìí pé, nítòótọ́ ìwọ ó jẹ ọba, àti pé ìjọba Ísírẹ́lì yóò sì fi ìdí múlẹ̀ ní ọwọ́ rẹ.

1 Sámúẹ́lì 24