1 Sámúẹ́lì 24:13-19 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

13. Gẹ́gẹ́ bí òwe ìgbà àtijọ́ ti wí, ìwá-búburú a máa ti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn búburú jáde wá; ṣùgbọ́n ọwọ́ mi kì yóò sí lára rẹ.

14. “Nítorí ta ni ọba Ísírẹ́lì fi jáde? Ta ni ìwọ ń lépa? Òkú ajá, tàbí eṣinṣin?

15. Kí Olúwa ó ṣe onídájọ́, kí ó sì dájọ́ láàrin èmi àti ìwọ, kí ó sì gbéjà mi, kí ó sì gbà mí kúrò lọ́wọ́ rẹ.”

16. Ó sì ṣe, nígbà tí Dáfídì sì dákẹ́ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí fún Ṣọ́ọ̀lù, Ṣọ́ọ̀lù sì wí pé, “Ohùn rẹ ni èyí bí, Dáfídì ọmọ mi?” Ṣọ́ọ̀lù sì gbé ohùn rẹ̀ sòkè, o sunkún.

17. Ó sì wí fún Dáfídì pé, “Ìwọ ṣe olódodo jù mí lọ; nítorí pé ìwọ ti fi ire san án fún mi, èmi fi ibi san án fún ọ.

18. Ìwọ sì fi oore tí ìwọ ti ṣe fún mi hàn lónìí: nígbà tí ó jẹ́ pé, Olúwa ti fi èmi mi lé ọ lọ́wọ́, Ìwọ kò sì pa mí.

19. Nítorí pé bí ènìyàn bá rí ọta rẹ̀, ó lè jẹ́ kí ó lọ ní àlàáfíà bí? Olúwa yóò sì fi ire san èyí ti ìwọ́ ṣe fún mi lónìí.

1 Sámúẹ́lì 24