21. Èmi yóò rán ọmọdékùnrin kan èmi yóò wí fún un wí pé, ‘Lọ, kí o lọ wá ọfà náà.’ Tí mo bá sọ fún-un wí pé, ‘wò ó, ọfà wọ̀nyí wà ní ibi báyìí ní ẹ̀gbẹ́ ẹ̀ rẹ;’ kó wọn wá síbí kí o sì wá, nítorí pé, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti wà ní ààyè, o wà ní àlàáfíà; kò sí ewú.
22. Ṣùgbọ́n tí mo bá sọ fún ọmọdékùnrin náà pé, ‘wò ó, àwọn ọfà náà kọjá níwájú rẹ;’ nígbà náà, o gbọdọ̀ lọ, nítorí Olúwa ti rán ọ jáde lọ.
23. Nípa ọ̀rọ̀ tí èmi àti ìwọ jọ sọ, rántí Olúwa jẹ́ ẹlẹ́rìí láàrin ìwọ àti èmi títí láéláé.”
24. Bẹ́ẹ̀ ni Dáfídì sá pamọ́ sínú pápá. Nígbà tí àṣè ìbẹ̀rẹ̀ oṣù tuntun sì dé, ọba sì jókòó láti jẹun.