1 Pétérù 2:1-3 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Nítorí náà, ẹ fi àrankan gbogbo sílẹ̀ ni apákan, àti ẹ̀tàn gbogbo, àti àgàbàgebè, àti ìlára, àti sísọ ọ̀rọ̀ buburú gbogbo.

2. Bí ọmọ ọwọ́ titun, kí ẹ máa fẹ́ wàrà ti Ẹ̀mí, èyí tí kò lẹ́tàn, kí ẹ̀yín lè máa tipasẹ̀ rẹ̀ dàgbà sí ìgbàlà.

3. nísinsìnyìí tí ẹ̀yín ti tọ́ ọ wò pé rere ni Olúwa

1 Pétérù 2