15. Olúwa sì wí fún un pé, “Padà lọ sí ọ̀nà tí ìwọ ti wá, kí o sì lọ sí ihà Dámásíkù. Nígbà tí ìwọ bá dé ibẹ̀, fi òróró yan Hásáélì ní ọba lórí Árámù.
16. Tún fi òróró yan Jéhù ọmọ Nímísì ní ọba lórí Ísírẹ́lì, àti kí o fi òróró yan Èlíṣà ọmọ Sáfátì, ará Ábélí-Méhólà ní wòlíì ní ipò rẹ.
17. Jéhù yóò pa ẹni tí ó bá sálà kúrò lọ́wọ́ idà Hásáélì, Èlíṣà yóò sì pa ẹni tí ó bá sálà kúrò lọ́wọ́ idà Jéhù.
18. Ṣíbẹ̀, Èmi ti pa ẹ̀ẹ́dẹ́gbàarin (700) ènìyàn mọ́ fún ara mi ní Ísírẹ́lì, àní gbogbo eékún tí kò ì tíì kúnlẹ̀ fún òrìṣà Báálì, àti gbogbo ẹnu tí kò ì tí ì fi ẹnu kò ó ní ẹnu.”