7. Ọ̀rọ̀ Olúwa sì wá nípa ọwọ́ Jéhù wòlíì ọmọ Hánánì pẹ̀lú sí Bááṣà àti ilé rẹ̀, nítorí gbogbo búburú tí ó ti ṣe níwájú Olúwa, ní mímú un bínú nípa ohun tó ti ṣe àti wíwà bí ilé Jéróbóámù: àti nítorí tí ó pa á run pẹ̀lú.
8. Ní ọdún kẹrìndínlọ́gbọ̀n Áṣà ọba Júdà, Élà ọmọ Bááṣà bẹ̀rẹ̀ sí ní jọba ní Ísírẹ́lì, ó sì jọba ní Tírísà ní ọdún méjì.
9. Ṣímírì, ọ̀kan nínú àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, olórí ìdajì kẹ̀kẹ́ rẹ̀, dìtẹ̀ sí i. Élà sì wà ní Tírísà nígbà náà, ó sì mu àmupara ní ilé Árísà, ìríjú ilé rẹ̀ ni Tírísà.