13. Ọba sì fi ohùn líle dá àwọn ènìyàn lóhùn, ó sì kọ ìmọ̀ràn tí àwọn àgbààgbà fún un,
14. Ó sì tẹ̀lé ìmọ̀ràn àwọn ọmọdé, ó sì wí pé, “Baba mí sọ àjàgà yín di wúwo; Èmi yóò sì jẹ́ kí ó wúwo sí i; Baba mi fi pàsán nà yín; Èmi yóò fí àkéekèe nà yín.”
15. Bẹ́ẹ̀ ni ọba kò sì fi etí sí ti àwọn ènìyàn, nítorí tí ọ̀ràn náà ti ọwọ́ Olúwa wá láti mú ọ̀rọ̀ tí ó sọ fún Jéróbóámù ọmọ Nébátì láti ẹnu Áhíjà ará Ṣílò ṣẹ.
16. Nígbà tí gbogbo Ísírẹ́lì rí i pé ọba kọ̀ láti gbọ́ ti àwọn, wọ́n sì dá ọba lóhùn pé:ìpín wo ni àwa ní nínú Dáfídì,Ìní wo ni àwa ní nínú ọmọ Jésè?Padà sí àgọ́ rẹ, ìwọ Ísírẹ́lì!Bojútó ilé ara rẹ, ìwọ Dáfídì!Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ará Ísírẹ́lì padà sí ilé wọn.
17. Ṣùgbọ́n fún ti àwọn ọmọ Ísírẹ́lì tí ń gbé nínú ìlú Júdà, Réhóbóámù jọba lóri wọn síbẹ̀.
18. Réhóbóámù ọba rán Ádórámù jáde, ẹni tí ń ṣe olórí iṣẹ́ irú, ṣùgbọ́n gbogbo Ísírẹ́lì sọ ọ́ ní òkúta pa, Réhóbóámù ọba, yára láti gun kẹ̀kẹ́ rẹ̀, ó sì sá lọ sí Jérúsálẹ́mù.
19. Bẹ́ẹ̀ ni Ísírẹ́lì ṣọ̀tẹ̀ sí ilé Dáfídì títí di òní yìí.