35. Nígbà náà ni kí ẹ sì gòkè pẹ̀lú rẹ̀, kí ó sì wá, kí ó sì jókòó sórí ìtẹ́ mi, kí ó sì jọba ní ipò mi. Èmi ti yàn án ní ọba lórí gbogbo Ísírẹ́lì àti Júdà.”
36. Bénáyà ọmọ Jéhóíádà sì dá ọba lóhùn pé, “Àmín! Kí Olúwa Ọlọ́run Olúwa mi ọba, kéde rẹ̀ bẹ́ẹ̀
37. Bí Olúwa ti wà pẹ̀lú Olúwa mi ọba, bẹ́ẹ̀ ni kí ó wà pẹ̀lú Sólómónì kí ó lè mú kí ìjọba rẹ̀ pẹ́ ju ìtẹ́ Olúwa mi Dáfídì Ọba lọ!”
38. Nígbà náà ni Sadókù àlùfáà, Nátanì wòlíì, Bénáyà ọmọ Jéhóiádà, àwọn ará Kérétì àti Pélétì sì sọ̀kalẹ̀ wá wọ́n sì gbé Sólómónì gun ìbaka Dáfídì ọba wá sí Gíhónì.