4. Ọ̀rọ̀ ọba, bí ó ti wù kí ó rí, borí tí Jóábù. Bẹ́ẹ̀ ni Jóábù kúrò ó sì jáde lọ sí Jérúsálẹ́mù.
5. Jóábù sì sọ iye tí àwọn ajagun ọkùnrin náà jẹ́ fún Dáfídì. Ní gbogbo Ísírẹ́lì, ó sì jásí ẹgbẹ̀rún ẹgbẹ̀rún àti ọ̀kẹ́ márùn-ún ènìyàn (Mílíọnù kan àti ẹgbẹ̀rún ní ọ̀nà ọgọ́rùn-ún) tí ó lè mú idà àti pẹ̀lú ọ̀kẹ́ mẹ́talélógún lé ẹgbàrún ní Júdà.
6. Ṣùgbọ́n Jóábù kó àwọn Léfì àti Bẹ́ńjámínì mọ́ iye wọn, nítorí àsẹ ọba jẹ́ ìríra fún un.