1 Kíróníkà 18:6-9 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

6. Ó sì fi àwọn ọ̀wọ́ ọmọ-ogun rẹ sínú ìjọba Áráméánì ti Dámásíkù, àwọn ará Áráméánì sì ń sìn ní abẹ́ Rẹ̀, wọ́n sì mú owó ìsákọ́lẹ̀ wá. Olúwa sì ń fún Dáfídì ní ìṣẹ́gun ní ibi gbogbo tí ó bá lọ.

7. Dáfídì mú apata wúrà tí àwọn ìjòyè Hadadésérì gbé, ó sì gbé wọn wá sí Jérúsálẹ́mù.

8. Láti Tébà àti Kúnì, ìlú tí ó jẹ́ ti Hádádéṣérì, Dáfídì mú ọ̀pọ̀ tánganran tí Ṣólómónì lò láti fi ṣe òkun tan-gan-ran, àwọn òpó àti orísìí ohun èlò tan-gan-ran.

9. Nígbà tí Tóù ọba Hámátì gbọ́ pé Dáfídì ti borí gbogbo ọmọ ogun Hádádéṣérì ọba Ṣóbà.

1 Kíróníkà 18